BBC News, Yorùbá - Ìròyìn
Ìròyìn tó ṣe kókó
Ohun tí a mọ̀ rèé nípa ìṣẹ̀lẹ̀ ọkùnrin tó 'gún ìyàwó rẹ̀ pa' tóun náà sì pa ara rẹ̀ l'Ogun
Bo tilẹ jẹ pe ileeṣẹ ọlọpaa ipinlẹ Ogun ti fesi lori iṣẹlẹ naa tẹlẹ, iyalẹnu lo ṣi n jẹ fun ọpọ awọn to n gbọ nipa iṣẹlẹ ọhun.
Fídíò, Orúkọ ọkọ mi ló wà níbi gbogbo dúkìá tí a ní, àmọ́ mi ò ri rò-Kemi Fajana,ìyàwó tó bá ọkọ rẹ̀ da òwò pọ̀, Duration 3,49
Abilekọ Fajana fi kun un pe ọkọ oun jẹ akinkanju nigba ti oun fẹ ẹ, yara kan ṣoṣo lo n gbe, o si n ta simẹnti ti ko ju aadọta apo lọ.
''Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ti wà lójúfò fáwọn agbébọn tó ṣèlérí láti ṣèkọlù sí Ikoyi-Ile l'Ogbomoso''
Alukoro ileeṣẹ ọlọpaa Naijiria, CSP Benjamin HUndeyin, lo fọrọ yii lede loju opo X rẹ.
Kókó nǹkan méje tí Chimamanda ń béèrè lọ́wọ́ ilé ìwòsan Euracare lórí ikú ọmọ rẹ̀
Ọmọdekunrin naa, Nkanu Nnamdi ku sile iwosan niluu Eko lẹyin aisan ranpẹ, eyii to da omi tutu sọkan awọn mọlẹbi rẹ.
Fídíò, Ṣíṣe bíi Quadri kò ki í ṣe ohun tí mo ní lọ́kàn tẹ́lẹ̀, ìdí rèé- Taooma, Duration 3,51
O ni oun ko ni lọkan pe oun yoo ṣe ẹda itan Quadri ṣugbọn oun to fẹ wa, to si jẹ ohun ti awọn eeyan
Orin, Kò ṣe é má gbọ̀ ọ́, Duration 0,59
Kò ṣeé má gbọ̀ọ́
Ìpínlẹ́ Katsina ṣàlàyé ìdí tó fi fẹ́ẹ́ tú agbésùnmọ̀mí 70 sílẹ̀
Ijọba ṣapejuwe igbesẹ gẹgẹ eyi ti yoo fayegba jiroro alaafia laarin ijọba ati awọn agbesunami.
Gbas-gbos ní ìpínlẹ̀ Rivers àti àtunbọ̀tán òṣèlú bàbá ìsàlẹ̀ nínú òṣèlú Nàìjíríà
Wo awọn ipinlẹ ti ija ti waye laarin gomina ati baba isalẹ rẹ, eyii to da rogbodiyan silẹ laarin ilu.
Ibi tí ìgbésẹ̀ yíyan Awujale tuntun dé dúró rèé
Idile naa fikun pe ijoko ipade ti yoo waye ni ọjọ Aje ni awọn ti yan awọn ọmọ oye ti wọn yoo fi orukọ wọn ransẹ si awọn Afọbajẹ.
Bí ẹbí Fusengbuwa ṣe yọ mí kúrò nínú Ọmọ-Oye fún ìtẹ́ Awujale Ijebu lòdì sófin, KWAM 1 kọ lẹ́tà sí Gómìnà
Ninu lẹta ti K1 fi ranṣẹ si Gomina Abiodun nipasẹ agbẹjọro rẹ, Wahab K. Shittu (SAN) lọjọ kẹjọ oṣu Kinni yii, gbajugbaja olorin Fuji naa sọ pe ki ẹbi Fusegbuwa ṣe agbeyẹwo awọn ofin to rọ mọ iyansipo ọba tuntun sori itẹ Awujale, ki wọn si foun naa lanfaani lati dupo ọhun.
Tí Trumpov bá ṣèkọlù sí Iran, a ṣetán láti gbẹ̀san lára Amẹrika - Ìjọba Iran
Adari ile aṣofin Iran sọ fawọn akẹgbẹ rẹ nile wi pe Iran ṣetan lati ṣe ikọlu si ibudo ologun Amẹrika to wa lẹkun Middle East ati si Israel, ti Amẹrika ba le ṣekọlu si Iran.
Iná jó èèyàn kan pa àti ilé 300 ní Australia
Iroyin ni fun ọpọ ọjọ ni ina ọhun fi jo kaakiri ilẹ naa, paapaa lagbe Victoria ati New South Wales.
Móríwú
BBC News Yorùbá ti wà lórí ìkànnì WhatsApp
Má jẹ́ kí etí rẹ ó di sí gbogbo ìròyìn ohun tó ń lọ ní Naijiria àti káàkiri àgbáyé. Mọ̀ nípa wọn lórí ìkànnì Whatsapp rẹ
Ìròyìn Àkàgbádùn
Wo bí Amala, moimoi, àtàwọn ọ̀rọ̀ míì ṣe wọ ìwé atúmọ̀ èdè Oxford àti ìtumọ̀ tí wọ́n fún wọn
Nínú àtẹ̀jáde ti oṣù Kejìlá, ọdún 2025 tí wọ́n fi léde lójú òpó ìtàkùn ayélujára wọn ṣàfihàn àwọn ọ̀rọ̀ tuntun tó lé ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta sínú ìwé atúmọ̀ èdè náà tó fi mọ́ DM, amala, moimoi, brainfart àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ.
Ìbànújẹ́ ni ikú Oluwafunlola Laisi jẹ́ sí àwa ẹbí ọkọ̀ rẹ̀ - Ẹ̀gbọ́n ọkọ̀ rẹ̀
Ọdun to kọja ni iroyin gbode lori iku arabinrin naa ati ọmọ rẹ eyi ti wọn ni ko sẹyìn bi ọrẹ rẹ kan ṣe tan-an lọ si ipinlẹ Osun lati ipinlẹ Ogun to ti n ṣiṣẹ, to si tan an lọ si ọdọ babalawo lati fi ṣe etutu ọla rẹ.
Kí nídìí táwọn olùwọ́de fi gba gbogbo ìgboro orílẹ̀ èdè Iran?
Ọjọ́bọ̀ ló pé ọjọ́ kejìlá tí ìwọ́de ti ń wáyé ní orílẹ̀ èdè náà látàrí bí owó ìlú náà ṣe ti já wálẹ̀ lọ́jà àgbáyé, tí ìwọ́de náà sì ti tàn káàkiri àwọn ìlú tó lé ní ọgọ́rùn-ún káàkiri ẹkùn mọ́kànlélọ́gbọ̀n tó wà ní orílẹ̀ èdè náà gẹ́gẹ́ bí àjọ tó ń rí sí ẹ̀tọ́ ọmọnìyàn ṣe sọ.
Ìjọba ilẹ̀ òkèrè dá $9.5m tí àwọn kan jí kó lọ sílẹ̀ wọn padà fún Naijiria
Owo ọhun ni iroyin sọ pe awọn kọlọrọsi ẹda ji ko lọ silẹ naa lọpọ ọdun sẹyin.
Ẹnikẹ́ni tí Allwell bá sẹ̀, ẹ dákun, ẹ forí jì í - Rotimi Salami dọ̀bálẹ̀ bẹ àwọn èèyàn
Ana ode yii ti i ṣe Ọjọbọ, ọjọ kẹjọ, oṣu Kin-in-ni ọdun 2026 ni eto isinku Oloogbe Allwell bẹrẹ ninu ọgba Tẹlifiṣan ipinlẹ Eko, nibẹ ni Rotimi Salami si ti ṣe ohun to jọ gbogbo eeyan loju nitori Allwell.
NCC fẹ máa da owó padà fáwọn oníbàárà tí kò bá rí káàdí ìpé lẹ́yín ìṣẹ́jú àáyá ọgbọ̀n tí wọ́n yọ owó wọn
Itumọ eyi ni pe nigba ti wọn ba ti yọ owo ẹni to fẹẹ ra kaadi, ṣugbọn ti ko ri kaadi, ko ni i ju iṣẹju aaya ọgbọ̀n (30 seconds) lọ ti wọn yoo fi da owo naa pada si akanti rẹ.
Àjọ NERC kéde pé Togo, Niger àti Benin ń jẹ Naijiria ní 25bn owó iná mọ̀nàmọ́ná
NERC sọ pe awọn orilẹeede naa jẹ Naijiria lowo yii nipasẹ ipese ina fun wọn, eyi to ni adehun ati ajọsọ ninu.
Àwọn orílẹ̀ èdè wo ni Trumpov tún ń fojúsùn lẹ́yìn Venezuela?
Ọ̀pọ̀ àwọn orílẹ̀ èdè ni Trumpov ti ń fojúsùn láti ṣe ìkọlù sí.
Ta ni Ọ̀mọ̀wé Olugbemisola Odusote, Adarí Obìnrin àkọ́kọ́ ilé ẹ̀kọ́ gíga àwọn Amòfin tí Tinubu ṣẹ̀ṣẹ̀ yàn sípò?
Atẹjade kan ti Oludamọran fun Aarẹ lori eto iroyin, Bayo Onanuga, fi sita lọjọ Iṣẹgun ana, fidi iyansipo naa mulẹ.
Àlàyé lórí òfin tuntun tí UK gbé kalẹ̀ lórí àwọn tó ń fi ọkọ̀ ojú omi káwọn àjèjì wọlé
Awọn ẹṣọ aṣọbode yoo maa gba foonu awọn to n lo ọkọ oju omi lati japa lọ si UK ni toootọ, amọ, eyi ko tumọ si pe wọn maa fọwọ ofin mawọn eeyan naa.
Kí làwọn àtúntò tí ìjọba Nàìjíríà mú bá ètò ìdánwò WAEC àti NECO láti dènà àwọn aṣemáṣe?
Ètò ìdánwò WAEC àti NECO ló wà fáwọn akẹ́kọ̀ọ́ ilé ẹ̀kọ́ girama tí wọ́n wà ní ipele àṣekágbá, tí wọ́n sì ń múra láti lọ sílé ẹ̀kọ́ gíga.
Ìjọba mi yóò rí i dájú pé irú ìkọlù yíì kò ṣẹlẹ̀ mọ́- Gómìnà Seyi Makinde
Gomina Makinde ṣalaye pe iwadii awọn ẹṣọ alaabo fi han, pe awọn agbesunmọmi to ti ẹnu ibode ibomiran wa lo ṣe iṣẹ ibi naa.
Ìròyìn Pàtàkì
Kọ́milẹ́kọ̀ọ́
Ẹ tẹ̀lé wa lórí ìkànnì ayélujára
Ìwádìí kíkún lóríi kókó ìròyìn
Kí nídìí tí ilé aṣòfin ìpínlẹ̀ Rivers fi bẹ̀rẹ̀ ìgbésẹ̀ láti yọ Gómìnà Fubara nípò?
Nígbà tó ń fìdí ìgbésẹ̀ náà múlẹ̀ pẹ̀lú ìwé òfin Nàìjíríà, Olórí ọmọ ilé tó pọ̀ jùlọ, Major Jack ka àwọn ìwà aṣemáṣe mẹ́sàn-án tó ní ó lòdì sí òfin.
Kí ni òfin tí Amẹ́ríkà ṣẹ̀ṣẹ̀ gbé kalẹ̀ fáwọn tó bá fẹ́ ṣe ìrìnàjò afẹ́ tàbí lọ ra ọjà níbẹ̀ láti Nàìjíríà?
Òfin yìí ló de àwọn tó bá fẹ́ gba físà B1 tàbí B2, tí wọ́n yóò sì máa san owó tí iye rẹ̀ fẹ́ẹ̀ tó mílíọ̀nù méje sí mílíọ̀nù méjìlélógún náírà ($5,000 - $15,000) kí wọ́n tó le rí físà gbà.
Ìdìtẹ̀gbàjọba ní Burkina Faso forí sánpọ́n, Traoré móríbọ́ lọ́wọ́ ikú
Mínísítà fún ètò ààbò Burkina Faso, Mahamadou Sana nínú ìkéde tó ṣe sọ pé ológun kan Paul Henri Damiba ló gbìyànjú ìdìtẹ̀gbàjọba tí kò kẹ́sẹ járí náà.
'Àwọn ajínigbé dúnkokò láti gbẹ̀mí Kàbíyèsí tàbí ọmọ rẹ̀ tí wọn kò bá san N100m owó ìtúsílẹ̀'
Ẹniọwọ Ajayi ṣalaye pe kabiesi ni kawọn lọ wa ọgọ́rùn-ún kan mílíọ̀nù naira ti awọn ajinigbe naa n beere fun ni gbogbo ọna tawọn ba ti leri owo ni kawọn wa owo lọ nitori ẹmi awọn ti fẹ ẹ bọ.
Ìdí tí iléeṣẹ́ Nestle ṣe fẹ́ dáwọn oúnjẹ ọmọdé tó tà sita padà àti bí o ṣe lè mọ oúnjẹ náà
''A tọrọ aforijin lọwọ gbogbo obi, alagbatọ atawọn onibaara wa ti igbesẹ wa yii ba fa inira fun,'' Nestle lo sọ bẹẹ.
Ìjọba Kwara bẹ̀rẹ̀ ètò ìkẹ́kọ̀ọ́ lórí rédíò fáwọn akẹ́kọ̀ọ́ nítorí ìkọlù àwọn ajínigbé
Olohungbebe ní dídá àwọn akẹ́kọ̀ọ́ dúró sílé láwọn agbègbè tí ètò ààbò ti nílò àmójútó níbẹ̀ gidi jẹ́ ọ̀nà láti fi dá ààbò bo àwọn olùkọ́ àti akẹ́kọ̀ọ́ ní agbègbè náà.
America fẹ́ẹ́ pa mi nínú ìkọlù, wọ́n ní Boko Haram ni mi-Sheikh Gumi
Gumi ni America n kede pe oun fẹ gba Naijiria la, lati ba awọn agbesunmọmi ja, ṣugbọn awọn gan-an ni agbesunmọmi.
Lẹ́yìn oṣù mọ́kànlá, àwọn òṣìṣẹ́ ìjọba ìbílẹ̀ padà sẹ́nu iṣẹ́ nípìnlẹ̀ Osun
Ti ẹ ko ba gbagbe pe, ọjọ Keje, osu Keji ọdun 2025 ni awọn oṣiṣẹ ijọba ibilẹ ni ipinlẹ Osun ti lọ si ọfiisi gbẹyin latari ifanfa to n waye lori awọn alaga ijọba ibilẹ.
Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá bẹ̀rẹ̀ ìwádìí lórí pásítọ̀ Chris Okafor táwọn obìnrin fẹ̀sùn kan pé ó fipá báwọn lòpọ̀
Iléeṣẹ́ ọlọ́pàá ní pásítọ̀ náà, tó jẹ́ pásítọ̀ àgbà nínú ìjọ Mountain of Liberation and Miracles Ministries, ìpínlẹ̀ Eko máa kojú ìwádìí tó lágbára.








































































